International News - A Yoruba Perspective

From BBC


Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ti rí afurasí tó pa ọ̀rẹ́bìnrin rẹ̀, Killaboy, gbé padà sí Nàìjíríà láti Qatar tó sálọ
Àtẹ̀jáde kan tí agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá Nàìjíríà, Olumuyiwa Adejobi fi léde sọ pé àjọṣepọ̀ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, iléeṣẹ́ tó ń rí sí ètò ìdájọ́ Nàìjíríà, àwọn ọlọ́pàá ilẹ̀ òkèèrè, (INTERPOL) , National Central Bureau àtàwọn aláṣẹ ètò ìdájọ́ ní Qatar lo ṣokùnfà bí wọ́n ṣe rí Benjamin dá padà sí Nàìjíríà.

Ọ̀pọ̀ èèyàn há sínú ilẹ̀ níbi ilé alájà mẹ́ta tó dàwó ní Eko
Ní agbègbè Oremeta, Ojodu-Berger ni ilé náà dàwó ní nǹkan bíi aago mẹ́jọ òwúrọ̀ gẹ́gẹ́ bí nǹkan táwọn tí ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣojú wọn ṣe sọ.

Gbajúmọ̀ olórin ẹ̀mí, Bolaji Olarewaju jáde láyé
Àtẹ̀jáde kan táwọn ẹbí olóògbé náà fi léde ṣàlàyé pé ọjọ́ Àbámẹ́ta ni akọrin ẹ̀mí náà dágbére fáyé.

Àdó olóró America pa èèyàn 74 níbùdó epo Yemen
Awijare ikọ ologun America lori ikọlu naa ni pe awọn ba ibudo epo Ras Isa naa jẹ lati dẹkun epo aitọ ti orilẹede Iran n ri nibẹ, ti wọn si n fi owo ibẹ ro awọn onijagidijagan Houthi lagbara.

VDM àtàwọn ọ̀dọ́ Arewa sọ̀kò ọ̀rọ̀ síra wọn lẹ́yìn tí Sultan Sokoto pe ayélujára nílé ìgbésùnmọ̀mí
VDM sọ pe kaka ki Sultan maa ti ẹnu bọ ọrọ ori ayelujara, niṣe lo yẹ ko lo ipo rẹ lati gbajumọ eto abo to dagẹgẹ ni Naijiria.

Ogún èèyàn tún kú nínú ìkọlù tuntun àwọn afurasí darandaran ní Benue
Alukoro ọlọpaa Benue sọ pe awọn ko mọ pe bawọn ṣe n gbiyanju lati le awọn darandaran lọ ni ikọlu mi-in tun n waye lagbegbe Logo.

Àlàyé rèé lórí ìdí tí ń kò fi ṣe àtìlẹyìn fún Peter Obi - Wike
Wike ni gẹgẹ bi oloṣelu, oun to gbajumọ ni agbara oludije lati bori eto idibo, ti oun ko ki n tẹle awọn oloṣelu to fẹ di olokiki lori ayelujara

Ṣó o láyà? Tope Osoba fakọyọ nínú ìmọ̀ èdè Yoruba
Tope Osoba gbiyanju, o si fi han pe ọmọ Yoruba atata ni ohun.

Mo pàdánù N10m sínú okoòwò CBEX - Taye Currency
Taye Currency ni awọn eeyan kan to sun mọ oun pẹkipẹki lo ni ki oun ko owo sinu okoowo sogun di ogoji naa.

Wo àwòrán bí àwọn Kristẹni ṣe ṣe àyájọ́ ọjọ́ Ẹtì rere
Saaju, awọn Kristẹni ma n ṣe ayajọ Ọjọ Ẹti rere pẹlu ibanujẹ ọkan, ti wọn si ma n fi ọjọ naa gba awẹ.

Ṣé lóòótọ́ ni ọkọ̀ tó kọ́wọ̀ọ́rìn pẹ̀lú aya Ààrẹ pa ọmọ ọdún méje l'Akure?
Ileeṣẹ ọlọpaa ni iwadii oun fihan pe ọkọ ayọkẹle mii ti ko ni nọmba lara lo gba ọmọ ọdun meje naa, to si jade laye lẹsẹkẹsẹ.

Afurasí darandaran jí akẹ́kọ̀ọ́ fásítì mẹ́wàá tó ń lọ fún ìpàdé Ajinde gbé lọ, méjì fara gbọta, wọn ń bèèrè N15m lọ́wọ́ ẹbí
Ọkan lara awọn akẹkọọ meji to fara gbọta ni a gbọ pe o wa lẹsẹ kan aye ẹsẹ kan ọrun bayii nile iwosan nibi ti wọn ti ṣe iṣẹ abẹ pajawiri lati yọ ọta ibọn lara rẹ.

Ìdásílẹ̀ ìgbìmọ̀ Sharia lè da àlàáfíà ilẹ̀ Yorùbá rú, àtúntò ìjọba lọ̀nà àbáyọ - Gani Adams
Aarẹ Onakakanfo ilẹ Yoruba sọ pe igbesẹ yii le da rukerudo silẹ, o si tun le jẹ kawọn alakata ẹsin dide gẹgẹ bi o ti n ṣẹlẹ lapa ariwa Naijiria.

Darapọ̀ mọ́ wa lórí WhatsApp
Má jẹ́ kí etí rẹ ó di sí gbogbo ìròyìn ohun tó ń lọ ní Naijiria àti káàkiri àgbáyé. Mọ̀ nípa wọn lórí ìkànnì Whatsapp rẹ

"Kò sí ẹnìkankan tó ń gbé ní ìjọba ìbílẹ̀ kan mọ́ torí Boko Haram, a kò le lọ ra oúnjẹ láì sí ológun lẹ́yìn wa, inú ìbẹ̀rù là ń gbé"
Àwọn èèyàn tó ń gbé ní agbègbè yìí sọ fún BBC News Pidgin pé láti ọdún mẹ́fà sẹ́yìn ni àwọn ti ń gbé lábẹ́ àkóso Boko Haram àti Iswap, tó sì jẹ́ pé inú fu àyà fu ni àwọn fi ń gbé ayé.

Ọmọdékùnrin tó dúró síwájú ọkọ̀ Peter Obi lásìkò ìpolongo ìbò 2023 gba ìtúsílẹ̀ lẹ́yìn oṣù mẹ́ta lọ́gbà ẹ̀wọ̀n
Ní ọjọ́bọ̀, ọjọ́ Kẹtàdínlógún, oṣù Kẹrin ni adájọ́ ilé ẹjọ́ Májísíréètì Apapa sọ pé kí Alabi máa lọ sílé rẹ̀ láyọ̀ àti àlááfíà lẹ́yìn tó gba àmọ̀ràn iléeṣẹ́ Director of Public Prosecutions tí ìpínlẹ̀ Eko.

Wo ìgbésẹ̀ tí iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ń gbé lórí fídíò tó ṣàfihàn àwọn ọlọ́pàá tó ń gbowó lọ́wọ́ ọmọ ilẹ̀ China
Ọpọ eeyan lo ti bu ẹnu ẹtẹ lu ihuwasi awọn ọlọpaa MOPOL ọhun ti wọn ni wọn n ṣiṣẹ pẹlu ileeṣẹ iwakusa ti orilẹede China kan to wa ni Sagamu nipinlẹ Ogun.

Àwọn obìnrin tí wọn bí lóbìnrin nìkan ni òfin rí gẹ́gẹ́ bíi obìnrin - Ilé ẹjọ́ tó ga jùlọ ní UK
Ẹgbẹ kan to n ri si ọrọ awọn obinrin ni Scotland lo gbe ijọba orilẹede naa lọ sile ẹjọ wi pe ko paṣẹ pe awọn ti wọn bi lobinrin nikan lo yẹ ki ofin maa ri gẹgẹ bii obinrin.

Wo ìdí tí wọ́n fi n pé ayájọ́ ọjọ́ 'Good Friday' ní orúkọ náà
Fun ọdun 2021, oni yii, tíì ṣe ọjọ Keji, oṣù Kẹrin ni ọjọ Ẹti rere fun ọdun yii bọ si, ti wọn n pe ni Good Friday.

"Lẹ́yìn oṣù díẹ̀ tí mo ṣe ìgbeyàwó ni mo bẹ̀rẹ̀ sí tọ̀ sílé pada"
Awọn onimọ sọ pe ko si oogun iyanu kankan to le wo aisan naa san lara bi kii ṣe pe ki eeyan maa sọ igbe aye rẹ nipa ohun to n jẹ ati to n mu.

Kí ni ìwọ̀n omi tó yẹ tàbí pọ̀ jù fún èèyàn lójúmọ́?
Pupọ ninu ohun ti a n jẹ lo ni ọpọ omi lara, fun apẹrẹ, eso watermelon ti ida 94% rẹ jẹ kiki omi.

Àwọn obìnrin 'Blue Origin' tó lọ sínu òfurufú padá sí orílẹ̀ ayé
Lẹyin ti wọn pada si ori ile aye, Perry ni oun ni tun ni ajọsepọ nla pẹlu ile aye ati pẹlu ifẹ si.

Akẹ́kọ̀ọ́ fásitì OAU gan mọ́ iná lásìkò tó ń gbá bọ́ọ̀lù
‎Iwadi BBC Yoruba fihan pe ọdọmọkunrin naa n gba bọọlu pẹlu akẹẹgbẹ rẹ nilegbe awọn akẹkọ naa, to si fori ko waya ina mọnamọna, to gba ẹmi rẹ.

Ṣé lóòtọ́ọ́ làwọn báǹkì àtàwọn ilé ẹ̀kọ́ gíga ń hùwà ìwà ìbájẹ́ nídìí pínpín owóyàá akẹ́kọ̀ọ́ tí Tinubu gbé kalẹ̀?
Laipẹ yii ni ajọ National Orientation Agency (NOA) ati Nigerian Education Loan Fund (Nelfund), kede pe magomago kan n waye nipa ẹyawo naa.

Àbọ̀ ìwádìí rèé lórí ohun tó mú kí owó tòmátò gbẹ́nu sókè, táwọn àgbẹ̀ fi ń kérora gbèsè
Ọpọ awọn agbẹ ni ọrọ yii ti kan, paapaa awọn ti wọn ti ko owo nla sinu ọgbin tomato ṣaaju ki kokoro too de.

Portable wọ wàhálà míì n‘Ilorin lórí gbèsè N6.3m owó eré tó gbà láì ṣe àmọ́...
BBC Yoruba gbera lọ si ile itura Starwood 02 Arena, Ilorin, lati mọ idi ti wọn fi n wa Portable ni pato ati igbesẹ wọn lori ati mu-un.

N1.3trn l‘ọmọ Nàíjíríà sọnù sínú okoòwò CBEX, a ṣetán láti fojú àwọn aṣebi hàn - EFCC
Agbẹnusọ fun ajọ EFCC, Dele Oyewale ni ajọ naa yoo fọwọsowọpọ pẹlu ajọ ọtẹlẹmuyẹ Interpol lati fi oju awọn asebi yii

N kò jẹ̀bi kíkun Afsot Yetunde wẹ́lẹ́wẹ́lẹ́ àti ẹ̀sùn mẹ́rin míràn tí ẹ fi kàn wá - Abdulrahman àtàwọn afurasí míì sọ̀ fún iléẹjọ́
Ìgbẹ́jọ́ Abdulrahman Bello, afurasi ti wọn fẹsun kan pe o ṣekupa Afsot Yetunde Lawal bẹrẹ nílé ẹjọ gíga ipinlẹ Kwara lonii ọjọ Iṣẹgun, ọjọ Kẹẹdogun, oṣu Kẹrin, ọdun 2025.

Russia rọ̀jò àdó olóró sórí Ukraine, èèyàn 34 kú, 117 míì farapa
Titi di asiko ti a n ko iroyin yii jọ, ijoba Russia ko tii sọ nnkankan nipa ikọlu ọhun.

Eniola Badmus àti Laide Bakare fìjà pẹ́ẹta níbi ìfilọ́lẹ̀ fíìmù Eniola Ajao
Níbi ìfilọ́lẹ̀ fíìmù gbajúmọ̀ òṣèré Eniola Ajao, Owambe Thieves tó wáyé ní agbègbè Lekki, ìpínlẹ̀ Eko ní ìṣẹ̀lẹ̀ náà ti wáyé.

Wo àwùjọ tí àwọn ìyà ti ń bẹ̀bẹ̀ ọkọ fún àwọn ọmọ wọn obìnrin
Ni ibẹrẹ ọdun yii, ileto kekere kan lẹkun ila oorun Zhejiang kede pe awọn yoo fun awọn lọkọlaya ni ẹgbẹrun kan yuan owo ilẹ naa (iyẹn dọla mẹtadinlogoje $137) gẹgẹbi ẹbun owo bi ọjọ ori iyawo ninu igbeyawo bẹẹ ko ba ti ju ọdun marundinlọgbọn lọ.

Portable wọ wàhálà míì n‘Ilorin lórí gbèsè N6.3m owó eré tó gbà láì ṣe àmọ́...
BBC Yoruba gbera lọ si ile itura Starwood 02 Arena, Ilorin, lati mọ idi ti wọn fi n wa Portable ni pato ati igbesẹ wọn lori ati mu-un.

Wo àwọn fóònù tí WhatsApp kò ní bá ṣiṣẹ́ mọ́ láti oṣù tó ń bọ̀
Ileeṣẹ Meta gbegi le awọn foonu kan lati maa lo Whatsapp lati ri pe awọn onibaara n gbadun aapu naa daadaa.

Ààrá sán pa èèyàn mẹ́ta ní ọjà ìrẹsì, márùn míì farapa
Fidio kan ti kọkọ gba ori ayelujara, ninu eyii ti ọkunrin kan ti n pariwo pe ara san pa eeyan meje ninu ọja naa, eyi lo mu ki BBC se abẹwo sibi isẹlẹ naa.

BBC dọ́gbọ́n fi fóònù ya àṣírí àti ìbẹ̀rù tó gbilẹ̀ ni Sudan, ìlú tó wà nínú ìdè ogun
BBC túnàṣírí àti ìbẹ̀rù tó gbilẹ̀ ni Sudan, ìlú tó wà nínú ìdè ogun

Wo àwọn okoòwò sogúndogójì tó ti lulẹ̀ ní Naijiria láti ọ́dún mẹ́wàá sẹ́yìn
Lopin ọsẹ to kọja ni ọpọ ọmọ Naijiria bẹrẹ si ni sọrọ lori itakun ayelujara wi pe awọn ti padanu owo rọgun-rọgun nibi okowo ki wọn pe orukọ rẹ ni CBEX.

Wo ìgbésẹ̀ ti Tinubu fẹ́ gbé láti mú kí oúnjẹ sùn wá bọ̀ ní Nàíjíríà
Tinubu rọ awọn ọmọ ilẹ Afirika lati ṣe amulo eto ọgbin lọna igbalode nipa ipese omi fun nnkan papaa julọ lasiko ọgbẹlẹ.

Ẹ múra sílẹ̀ fún òjò ọlọ́jọ́ mẹ́ta pẹ̀lú ìjì líle àti àrá - Nimet
Ni ọjọ Iṣẹgun, ajọ Nimet ni oorun yoo jade lọpọ agbegbe ni ẹkun ariwa Naijiria, amọ, o ṣee ṣe ki ara san lasiko ti ojo ba n rọ ni ipinlẹ Kaduna, Taraba ati Adamawa lọsan tabi lalẹ.

HUMILITASCharleans' Contribution Worldwide

300

Charlean Doctors

250

Charlean Engineers

150

Charlean Lawyers

109

Charlean Professors

We always perform at our best when we work together

Our mission is to provide the means & technical know-how to accomplish the aforementioned with HUMILITAS - always