Our Services



News From The BBC

A Yoruba Perspective


Àṣìta àdó olóró míràn tún ti wáyé, ẹ̀mí márùn ún ló lọ síi
Awakọ alaisan, akọle wa lara eeyan mẹta to padanu ẹmi wọn.

Gbogbo àwọn ọmọ wa ni omíyalé ti ṣekúpa, aráàlú pariwo síta
Marieta Banga sọ fun BBC pe eeyan mẹjọ ninu mọlẹbi rẹ lo padunu wọn lẹyin isẹlẹ omiyale to waye ni apa ariwa Tanzania.

Torí ìjèrè ọkàn ni mo ṣe pe Portable àti Pasuma sí àṣálẹ́ ankara – Oluṣọ ijọ Celestial
Dabiri, ninu alaye rẹ, wi pe eyi kii ṣe igba akọkọ ti oun yoo pe olorin aye lati waa bawọn jọsin ninu ijọ naa.

Forbes kéde Ngozi Okonjo-Iweala, Mo Abudu, àwọn obìnrin méjì míràn láti Áfíríkà lára àwọn obìnrin 100 tó lẹ́nu jùlọ lágbáyé
Ni ti ọdun yii, ọmọ ilẹ adulawọ mẹrin, ti ọmọ Naijiria meji wa ninu wọn ni Forbs kede.

Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ afurasí tó gé orí, ọwọ́, ọkàn àti ẹsẹ̀ akẹ́kọ̀ọ́ OAU
Agbẹnusọ ileeṣẹ naa, Omolola Odutola lo fi ọrọ naa lede ninu atẹjade to fi ṣọwọ si awọn akọroyin.

Ìjọba Nàìjíríà ń dọ́gbọ́n láti da ọwọ́ bo ìdadìí ikọlù àdó olóró t’ólógun jù s’áráàlú ní Kaduna
Ọpọ ẹhonu lo ti jade si bi baalu Díronu ijagun ileeṣẹ ọmọogun oriilẹ ni Naijiria ṣe ju ado oloro si aarin awọn eeyan ileto naa lasiko ti wọn fi n ṣe ajọyọ Maulud Nabiyy lopin ọsẹ to kọja.

Agbébọn ṣíná ìbọn bolẹ̀ nínú ọgbà fásitì, èèyàn mẹ́ta jáde láyé
O ti le ni igba 630 ti araalu ti ṣina ibọn bọle nilẹ Amẹrika lọdun yii nikan ṣoṣo.

Wáá gbọ́ ohun tí àwọn èèkàn ìlú n sọ nípa àdó olóró tó pa ọ̀pọ̀ ní Tundun Biri
Akọlu ọhun, ti ajọ ologun ilẹ naa pe ni aṣiṣe, lo mu ọpọlọpọ ẹmi lọ ti awọn miran si n gba itọju nileewosan.

Inú àgbàrá ẹ̀jẹ̀ la ti gbé òkú ọmọbìnrin ọdún mẹ́tàdínlógún kan lẹ́yìn tí 'ọmọ Yahoo' kan fipá bàa lòpọ̀ ní Ilorin
Ileetura kan ni ọmọ 'yahoo' kan ti fipa baa lo pọ to si fẹẹ sa lọ lẹyin to ku tan

‘Láti kékeré la ti ń pe Ọọ̀ni Ogunwusi ní Ọọ̀ni, Wòlíì kan ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa bí yóò ṣe jọba ṣáájú ìbí rẹ̀’
Baba Ọba tun sọ omii pe baba oun gan ti ni ki awọn ma maa fi ọwọ gba a lori toripe ori ade ni.

Frank Kokori, èèkàn láàrín àwọn tó jà fún ìdápadà ìjọba alágbádá ní Nàìjíríà jáde láyé
Ni ọjọ to yẹ ki gbajugbaja ajafẹtọ araalu naa ṣe ayẹyẹ Ọjọ ibi ọgọrin ọdun rẹ lo dagbere faye.

Èèyàn 4.8 mílíọ̀nù ni ebi ń pa, iléẹ̀kọ́ 9000 di títìpa nítorí ọ̀rọ̀ àbò tó mẹ́hẹ - Ecowas
Touray wi pe ẹtalelẹẹdẹgbẹjọ ni akọlu awọn agbesunmọmi to ti waye ni Burkina Faso lati ọjọ kini oṣu kini si ọjọ kejilelogun oṣu kẹwa ọdun yii.

Ṣe lóòtọ́ ni ìjọba àpapọ̀ ya ₦10b sọ́tọ̀ fún àtúnṣe ilé Femi Gbajabiamila nínú ètò ìṣúná ọdún 2024?
Gbajabiamila lo fi ọrọ naa lede ninu atẹjade kan loju opo X rẹ.

Ṣé lóòótọ́ ni Ooni lọ ṣe àbẹ̀wò sí Emefiele lọ́gbà ẹ̀wọ̀n?
Agbẹnusọ Ooni, Otunba Moses Olafare sọ fun BBC pe ohun iyalẹnu lo jẹ nigba ti oun ri iroyin to n lọ kaakiri pe Ooni ṣe abẹwo si Emefiele.

“Adarí ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin Ondo, wá sọ ìdí tí o kò fí ni gbé ìgbìmọ̀ dìde láti ṣe àyẹ̀wò ìlera Akeredolu”
Agbẹjọro fun awọn olupẹjọ naa, Olukayode Mogbojuri, wi pe ohun ti awọn onibara oun n fẹ ni lati mọ ipo ti gomina ti wọn dibo yan wa ni tootọ.

Owó ìsákọ́lẹ̀ fa làásìgbò láàrín àwọn Hausa nílùú Babanla ní Kwara
Ọpọ lo farapa yannayanna lọjọ Aiku, Sannde, ọjọ Kẹta, oṣu Kejila, ọdun 2023 ti isẹlẹ yii waye.

Iléẹjọ́ pàṣẹ fún orílẹ̀èdè Benin kó san ₦70.8m fún Sunday Igboho lórí ìtìmọ́lé lọ́nà àìtọ́
Idajọ yii lo waye lẹyin ti ile ẹjọ naa ni orilẹ-ede ọhun jẹbi bo ṣe ti Igboho mọle, ati pe o tun tẹ ẹtọ ọmọniyan rẹ loju mọlẹ.

'Orí ló kó èmi àti ìyàwó mi yọ, àwa náà ìbá kú nínú ìjàmbá ọkọ̀ tó gbẹ̀mí àwọn ọba mẹ́ta l'Ogbomoso'
Ọsẹ to kọja ni ọba alaye mẹta padanu ẹmi wọn ninu ijanba pẹlu ọkọ ayọkẹlẹ Benz E230 kan ati ọkọ akero Scania to ni nọmba idanimọ 301 XF loju opopona.

Ọ̀gá àgbà Iléeṣẹ́ ológun tọrọ àforíjìn lọ́wọ́ àwọn èèyàn Tudun Biriin
Ninu atẹjade kan ti Ileeṣẹ ologun fi sori opo ayelujara wọn, Ọga ologun sabẹwo si agbegbe naa lati ba awọn ara agbegbe naa kẹdun lori isẹlẹ naa.

Èmi ò kán ọrùn Mohbad, irọ́ layé ń pa mọ́ mi, ìbátan rẹ̀ Darosha fi'gbe ta
Ikú akọrin takasufe Mohbad jẹ nkan to mi igboro titi ti awọn ololufẹ rẹ si ni ki wọn ṣe iwadii iku rẹ.

Èèyàn 422 ni a kó lọ síbi àpérò àyípadà ojú ọjọ́ COP28 ní Dubai, kíì ṣe 1,411 – Ìjọba àpapọ̀
Ipade COP28 ọhun ni awọn olori orilẹ-ede lagbaye ti n jiroro lona ati dojukọ iṣoro ti ayipada ou ọjọ n fa, atawọn nnkan mii.

Ọ̀pọ̀ àwọn olùkọ́ wa ló ń kọ̀wé fi ipò sílẹ̀ láti Japa nítorí ìyà tó ń jẹ wọ́n – ASUU
Alaga ẹgbẹ naa ni fasiti ijọba apapọ to wa niluu Ibadan, UI, Ọjọgbọn Ayo Akinwole lo sọ bẹẹ niluu Ibadan.

Ohun gbogbo ti bàjẹ́ kọjá àlà nílé ìwòsàn Gaza bí àkọlù ṣe ń tẹ̀síwájú - Hamas
Agbẹnusọ ileeṣẹ eto ilera ti Hamas n dari nibẹ, Ashraf al-Qudra, wi pe oku mẹtalelogoji ni wọn ti ko wọ ileewosan naa laarọ ọjọ iṣẹgun nikan.

Israel bẹ̀rẹ̀ sí ń sọ àdó olóró sí Gaza lákọ̀tun, ọ̀pọ̀ òkú sùn
Israel ni oun ti kọlu agbegbe ti ko fdn ni 200 lati igba to ti bẹrẹ ikọlu naa pada lọjọ ẹti.

Gbogbo àkáǹtì tí kò bá ní NIN tàbí BVN la máa tì pa – CBN
Wọ́n ní àwọn akoto owó ni wọ́n gbọdọ̀ so àwọn nọ́ḿbà ìdánimọ̀ yìí pọ̀ mọ́ kó tó di ọjọ́ Kọkànlélọ́gbọ̀n oṣù Kìíní ọdún 2024.

Iléeṣẹ́ ààbò So-Safe lé òṣìṣẹ́ rẹ̀ kan fẹ́sùn olè jíjà
Àtẹ̀jáde tí Agbẹnusọ So-Safe, Moruf Yusuf fi léde ni wọ́n ti fi ìkéde náà síta pé ọ̀gá àgbà àjọ náà, Soji Ganzallo ti buwọ́lù ú pé kí wọ́n lé Adeboye Yusuf Sunday kúrò lẹ́nu iṣẹ́ ọ̀hún.

Ọ̀pọ̀ àwọn tó wá ń ṣe àyẹ̀wò DNA ni ilé wọn máa ń dàrú – Onímọ̀ nípa àyẹ̀wò DNA
Odedele ninu alaye rẹ ni DNA jẹ nnkan ti awọn eeyan n fi silẹ lati irandiran.

Babalawo tó di pásítọ̀ fún ìyàwó rẹ̀ lọ́rùn pa l’Ekiti, ó dèrò àtìmọ́lé
Alukoro ileeṣe ọlọpaa Ekiti, DSP Sunday Abutu, to fidi iroyin naa mulẹ fun BC Yoruba ṣalaye pe awọn ti bẹrẹ iwadii lori iṣẹlẹ naa.

Mọ́ṣọ́láṣì ìlú Inisa jẹ́ ṣíṣí lẹ́yìn ọdún mẹ́ta
Iwadii BBC News Yoruba ṣafihan pe lákòókò tí wọn fẹ yan Imam agba Mọsalasi naa iyẹn Chief Imam ni awuyewuye bẹ silẹ laaarin awọn to fẹ jẹ oye ọhun.

Tonto Dikeh fẹ̀sùn kan Baba Mohbad pé Ó ń gba ₦10k sí ₦15k kó tó ṣe ìfọ̀rọ̀wérọ̀, Baba Mohbad ní irọ́ ńlá ni
Bakan naa lo fẹsun kan Baba oloogbe pe o n wa gbogbo ọna lati gbesẹ le gbogbo ọrọ ti ọmọ rẹ fi silẹ laye.

Ọlọ́pàá wa'kọ̀ pa akẹ́kọ̀ọ́ kan l'Ogun, akẹ́kọ̀ọ́ mẹ́ta míì farapa
Alukoro ọlọpaa nipinlẹ Ogun Omolola Odutola sọ pe oun gbọ nipa iṣẹlẹ naa amọ oun ko le sọ pato nipa nkan to ṣẹlẹ.

Ìkọlù bẹ̀rẹ̀ padà láàrín Israel àti Hamas, lẹ́yìn wákàtí díẹ̀ tí gbèǹdéke ìdádúró ìjà parí
Ikọ ologun Israel Israel Defence Forces, IDF, sọ pe lọwọ lọwọ lawọn baalu ogun awọn n ju ado oloro lu awn aaye ibi ti Hamas wa ni Gaza.

Mi ò ní sinmi, àyàfi kí n fojú àwọn tó pá Taiwo Oyekanmi hàn fáyé rí - Dapo Abiodun
Abiodun ni inu ibanuje àti iporuru ọkan ni òun àti àwọn ọmọ igbimo ìṣàkóso ipinle Ogun wa láti ìgbà tí ìròyìn ikú Ogbeni Taiwo oyekanmi tí to òun létí.

Àwọn afurasí méjì tó ń jẹ́jọ́ lórí ikú ọ̀gá àgbà hòtẹ́ẹ̀lì n'Ilorin tún fojú ba'lé ẹjọ́
Saaju ni awọn obinrin meji yii jẹwọ pe awọn wọ inu yara kan ni inu ile itura kan pẹlu Adeniyi Ojo sugbon lẹyin isẹju diẹ wọn jade laisi Ojo pẹlu wọn.

A ò lọ́wọ́ nínú làásìgbò tó ń wáyé láàárín ìjọba Osun àti adájọ́ àgbà -Ẹbí Adedoyin
Agbẹnusọ ìdílé Adedoyin, Kunle Awojoodu ní kí ẹnikẹ́ni yé lo ìgbẹ́jọ́ Rahman Adedoyin láti fi bo ìwà àjẹbánu èyí tí wọ́n fi kan adájọ́ àgbà náà.

Ìjọba Ondo fọwọ́ sí àfikún owó oṣù ₦35k fáwọn òṣìṣẹ́, Osun fi ₦15k kún tiwọn
Owo yii ni awọn oṣiṣẹ naa yoo gba fun oṣu mẹfa gbako, lai fi ti ipo ti wọn wa lẹnu iṣẹ ṣe.

Nǹkan yan! Ìyá arúgbó ẹní ọdún 70 bí ìbejì, bàbá ọmọ f'ẹsẹ̀ fẹ́ ẹ
Ti a ba fi ibeji yi kun ọmọ obinrin kan to wa nilẹ tẹlẹ, o di ọmọ mẹta bayii ti Eledua fi ta arabinrin Namukwaya lọrẹ

Àwọn olólùfẹ́ ANPP wọ́de ní Kano, ìgbìmọ̀ ètò ìdájọ́ ní Nàìjíríà pinnu láti wádìí awuyewuye ìwe ìdájọ́ ìdìbò gómìnà níbẹ̀
Igbimọ naa wi pe gbogbo iwe ẹsun ti awọn araalu kọ ranṣẹ si awọn ni awọn ti ri, ti wọn yoo si ṣiṣẹ le lori bo ṣe yẹ.

Kí ni ìtumọ̀ ìdókòwò ọ̀tun fáwọn báńkì àti bó ṣe kan oníbàárà wọn?
Awọn ile ifowopamọ kan ti n duna dura bi wọn yoo ṣe pawọpọ ki wọn baa le kaju oṣunwọn nipa iye owo ti o wa lakata wọn.

Wo ìgbà mẹ́jọ ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ tí Iléeṣẹ́ ológun ti ṣèsì ju àdó olóró sí àárin àwọn aráàlú
Ileeṣẹ BBC se agbekalẹ awọn isẹlẹ to ti waye sẹyin ti asise ileeṣẹ ologun Nigeria ti gba ọpọlọpọ ẹmi.

Nàìjíríà fẹ́ ta bàlúù ààrẹ
Ajọ naa wi pe gbogbo eniyan to ba nifẹ si rira baaluu naa ni awọn pe ko fiwe ṣọwọ si wọn ni ibamu pẹlu ofin tita ati rira ẹru fun ileeṣẹ ati ijọba ti ọdun 2007.

Wo ọ̀nà tí o lè gbà láti kópa níbi àpérò COP28 ní Dubai làí tẹ̀lé ìjọba
Awọn oniṣowo pataki kọọkan kaakiri agbaye, awọn ileeṣẹ to lorukọ, awọn ileetaja, ọdọ, akọroyin ati ajafẹtọ lo lee wa nibẹ, bo tilẹ jẹ pe o loju ibi ti onikaluku ti lee kopa

'Google Map' kìí ṣe àwáwí bí o bá ṣìnà l’Eko, o máa fojú winá òfin – Ọlọ́pàá
Ọrọ naa lo waye lẹyin ti awakọ kan, Oyiga Micheal sọ lori ayelujara pe awọn ọlọpaa mu oun lagbagbe Ijesha, niluu Eko lori ẹsun pe oun n lo ẹrọ Google Map naa.

Àdó olóró búrẹ́kẹ lásìkò ìjọsìn àwọn Kátólíìkì, èèyàn mẹ́rin kú, 42 farapa
olori ileeṣe ọlọpaa lagbegbe naa, Brig Gen Allan Nobleza ni ẹgbẹ awọn Musulumi kan, Daulah Islamiyah-Maute Group ni awọn fura si pe o ṣeeṣe ko lọwọ ninu ikọlu naa.

Makinde ṣèdárò àwọn orí adé mẹ́ta tó jáde láyé nínú Ìjàmbá ọkọ̀ Oyo
Nigba to n fidi ijamba naa mulẹ, Joshua Adekanye to gba ẹnu ileeṣẹ ẹṣọ oju popo, FRSC sọrọ in ṣe ni ọkọ mejeji fori sọ ara wọn.

Àṣìta àdó olóró míràn tún ti wáyé, ẹ̀mí márùn ún ló lọ síi
Awakọ alaisan, akọle wa lara eeyan mẹta to padanu ẹmi wọn.

Àwọn ọmọ Naijiria 180,000 tó fẹ́ wá sílẹ̀ wa la ti ṣe ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò fún lọ́dún yìí – Ìjọba Amẹrika
Oluṣakoso ọọfisi ijọba ilẹ Amẹrika ni Naijiria, Ọgbẹni David Greene lo sọ ọrọ naa ninu ifọrọwerọ kan pẹlu ileeṣẹ iroyin News Agency of Nigeria, NAN, niluu Abuja.

Wo ọ̀nà tuntun tí àwọn afurasí ń lò láti gbé ògùn olóró
Ọwọ NDLEA tun tẹ arakunrin kan ẹni ọdun mẹrindinlọgọta, Okechukwu Ogala to jẹ baba isalẹ to maa n ko awọn ọdọ lati fi ṣe fayawọ oogun oloro lọ si awọn orileede ilẹ Asia.

Wo obìnrin àkọ́kọ́ ní South Africa tó jẹ́ olúkọ́ni nípa wíwẹ́ dé ìsàlẹ̀ odò
Ninu ifọrọwerọ rẹ pẹlu Ileeṣẹ BBC, Zandile Ndhlovu salaye bo ṣe bẹrẹ irin ajo rẹ to fi di akọnimọse.

Ìjọba Ekiti pe pásítọ̀ Chef Dammy lẹ́jọ́ lórí ẹ̀sùn ìdúnkokòmọ́ni, bèrè ₦10m owó gbá máb̀inú lọ́wọ́ rẹ̀
Eredi ipẹjọ naa ko ṣẹyin pe pasitọ ọhun atawọn ọlọpaa tẹ ẹtọ akẹkọọbinrin naa loju mọlẹ.

Kò síbẹ̀rù, ẹ máa ná owó náírà àtijọ́ papọ̀ mọ́ tuntun lọ - Ilé ẹjọ́ tó ga jùlọní Nàìjíríà
Ṣaaju ni banki apapọ ti kede lọjọ kẹrindinlọgbọn, oṣu kẹwaa ọdun 2022, pe oun yoo paarọ awọn owo naa si tuntun, opin yoo si de ba nina tatijọ lọjọ kọkanlelọgbọn oṣu kejila ọdun 2023 yii.

Kí lo fà á tí Iyabo Ojo fi fẹ́ wọ́ Lizzy Anjorin lọ sílé ẹjọ́?
Ajegbomogun ni nitori Iyabo nikan kọ ni oun ṣe n ṣe eleyi, amọ oun fẹẹ fi opin si idunkoko mọni lori ẹrọ ayelujara ni.

A ti ṣetán láti kó ọkọ̀ tó ń lo iná ẹlẹ́tírìkì 100 wọ Nàìjíríà - Tinubu
Tinubu ní kíkó àwọn ọkọ̀ náà wọlé yóò mú àdínkù tó lóòrìn bá àwọn nǹkan tó ń ba ojú ọjọ́ jẹ́ àti pé yóò pọkún ètò ìrìnnà Nàìjíríà.

Wo àwọn ọ̀nà to lè fi dá ààbò bo ilé rẹ lọ́wọ́ ejò lásìkò ọyẹ́
Kò sí àsìkò tí ejò kìí sán ènìyàn, tí oró rẹ̀ sì lè ṣekúpa ènìyàn tí wọ́n kò bá tètè rí aporó rẹ̀.

Ìjọba àpapọ̀ yóò bẹ̀rẹ̀ sí ní san owó oṣù tuntun ní oṣù kẹrin ọdún 2024- Minisita
Muhammad ni ijọba ti pese owo to le ni trilọnu mẹrinlelogun fun sisan owo oṣu awọn osisẹ lọdun 2024, 2025 ati ọdun 2026.

BBC 100 Women 2023: Àwọn wo ló wà nínú àkọsílẹ̀ obìnrin tó lààmì-laaka jùlọ ní àgbáyé lọ́dún yìí?
Ileeṣẹ BBC ti fi orukọ obinrin ọgọrun to n ṣe moriya fawọn obinrin ẹgbẹ wọn, ti wọn si tun gbajugbaja julọ lagbaye sita fun ọdun 2023.

Oṣù kínní ọdún 2024 lètò ẹ̀yáwó fawọn akẹ́kọ̀ọ́ yóò bẹ̀rẹ̀, Tinubu ṣàlàyé lórí ìṣúná 2024
Aarẹ lo sọ ọrọ yii lasiko to n ṣagbekalẹ eto iṣuna ọdun 2024 niwaju awọn aṣofin atawọn aṣojuṣofin niluu Abuja.

EFCC ṣàlàyé ọ̀nà mẹ́jọ tí o lè fi dènà àwọn tó bá fẹ́ fi ATM àti POS wọ́ owó lọ nínú àkáǹtì rẹ
Ajọ to n gbogun ti iwa ajẹbanu ni Naijiria, EFCC sọ pe awọn iwa jibiti yii maa n waye ti ọwọ awọn kọlọrọsi ẹda naa ba ti tẹ kaadi ATM eeyan.

Wo ìdí tí Godwin Emefiele, gómìnà báǹkì àpapọ̀ Nàìjíríà tẹ́lẹ̀, yóò fi ṣe ọdún Kérésìmesì ní àtìmọ́lé
Eyi ko sẹyin bi o ṣe kuna lati ri baali gba lọjọ Isẹgun, ọjọ kọkandinlọgbọn oṣu kọkanla ọdun 2023.

HUMILITASCharleans' Contribution Worldwide

300

Charlean Doctors

250

Charlean Engineers

150

Charlean Lawyers

109

Charlean Professors

We always perform at our best when we work together

Our mission is to provide the means & technical know-how to accomplish the aforementioned with HUMILITAS - always