Our Services



News From The BBC

A Yoruba Perspective


Wo ànfààní tó wà nínú jíjẹ́un làí kánjú
Bi eeyan ko ba jẹ ounjẹ lẹnu daadaa, yoo ṣoro fun ikun lati dà ounjẹ naa.

Àwọn agbébọn tún jí èrò inú ọkọ̀ méjì gbé lọ ní Kwara, ọlọ́pàá dóòlà méjì nínú wọn
Wọn ni awọn agbebọn naa di oju ọna, wọn si fipa gbe gbogbo ero to wa ninu awọn ọkọ naa lọ.

Tírélà jábọ́ láti orí afárá l'Eko, rún Korope méji pa
Atẹjade kan ti Adari iṣẹlẹ bi eyi ati ilaniloye ni LASTMA, Adebayo Taofiq, fi sita, sọ pe dẹrẹba to wa ọkọ tirela naa ko ni ikapa lori ọkọ ọhun mọ lasiko ijamba naa.

Mi ò kábàmọ́ọ̀ pé ìyàwó mi tó kú nigbà tó fẹ́ bímọ kò forúkọ sílẹ̀ nílé ìwòsàn - Folajimi
Ọgbẹni Akinbobola Folajimi sọ ninu ifọrọwanilẹnuwo to ṣe pẹlu BBC pe kii ṣe ile iwosan loun bi awọn ọmọ oun meji toun ti bi ṣaaju si.

''Èédú àti ewé ni àwọn èèyàn ń jẹ ni Sudan báyìí''
Ajọ oluranlọwọ kan lo fidi eyi mulẹ fun BBC.

Bí o ṣe le lo Etí Erin (Aloe Vera) fún ìṣaralóge àti ìwòsàn àgọ́ ara
Bi wọn ṣe n lo o fun iṣaraloge lo tun wulo fun ilera.

Akọrin tàkasúfèé, Terry Apala, di èèrò ẹ̀wọ̀n fún ẹ̀sùn pé ó tàbùkù owó náírà
Ajọ EFCC to n gbogun ti iwa ibajẹ ni Naijiria lo gbe Terry Apala lọ sile ẹjọ lori ẹsun onikoko kan to da lori ṣíṣe owo naira ni iṣekuṣe.

Wo ojú, orúkọ àti àwòrán àwọn afurasí ọmọ Naijiria tó ṣe agbódegbà fún CBEX
Adajọ Emeka Nwite lo gbe idajọ yii kalẹ ni Ọjọbọ, ọjọ kẹrinlelogun oṣu kẹrin ọdun 2025 lẹyin ti ajọ EFCC gbe ẹjọ naa wa si ile ẹjọ.

Ìdí pàtàkì tí àwọn pápákọ̀ ọkọ̀ òfurufú ṣe n gbẹ́kẹ̀lé àjọ tó ń wòye ojú ọjọ́
Awọn oṣiṣẹ Nimet ṣe iwọde niluu Eko níbi ti wọn ti gbe awọn beba dani ti wọn kọ oriiṣiriṣii ọrọ si lara bíi "Láì mọ bi oju ọjọ ṣe rí, baalu kò le fo."

Kí ni ọ̀nà àbáyọ bí ilé ìfowópamọ́ àgbáyé ṣe ní ìṣẹ́ àti òṣì máa pọ̀ si ní Nàìjíríà lọ́dún 2027?
Wọ́n ní èyí máa rí bẹ́ẹ̀ látàrí bí Nàìjíríà ṣe gbáralé epo rọ̀bì gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà kan gbòógì tó fi ń pawó wọlé, àìrajaja ètò ọrọ̀ ajé àti ìpèníjà ètò ìṣèjọba tó dúró ire.

ECOWAS ní kí Mali, Niger àti Burkina Faso fi àwọn iléeṣẹ́ wọn sílẹ̀
Níbi ìpàdé àwọn mínísítà fọ́rọ̀ ilẹ̀ òkèèrè àwọn orílẹ̀ èdè ECOWAS tó wáyé ní Ghana ni wọ́n ti sọ̀rọ̀ náà.

Ǹ jẹ́ ò ń fọ nǹkan ìmumi rẹ dáadáa bó ṣe yẹ?
Carl Behnke ni oun ma n ro bi ''Water Bottle" ti oun ma n tun lo ṣe mọ to. O ni nigba ti oun gbiyanju lati fi pepa nu, oun to jade ninu rẹ ya oun lẹnu.

Orí Adé dèrò ilé-ejọ̀ fún gbígba ilẹ̀ onílẹ̀, gba ọ̀pọ̀ mílíọ́nù naira lọ́wọ́ ẹnikan nípìnlẹ̀ Ogun
Ọba Owolabi, ẹni to jẹ ọmọ ẹgbẹ lọbalọba Egba, ni o foju ba ile ẹjọ lọjọ Isẹgun, ọjọ kejilelogun oṣu kẹrin ọdun 2025, ti ijọba si tun ni ko rọkun ile bayii.

Wo àwọn tó ṣeéṣe kí ọ̀kan nínú wọ́n di póòpù tuntun
Àkójọpọ̀ àwọn Cardinal yóò ṣèpàdé ní ilé ìjọsìn Sistine ní Vatican níbi tí wọ́n ti máa jíròrò, tí wọ́n sì máa dìbò yan títí tí ẹnìkan fi máa borí.

Ojúlówó ọmọ ijọ Celestial ni mí, kódà, mo kọ́ ṣọ́ọ̀ṣì CCC kan fúnra mi - K1 De Ultimate
Ọpọ lo gbagbọ wi pe ẹlẹsin musulumi pọnbele ni K1 pẹlu bi o ti n jẹ orukọ musulumi ti o si tun ti lọ si Mecca lai mọ iye igba fun iṣẹ Hajj.

Darapọ̀ mọ́ wa lórí WhatsApp
Má jẹ́ kí etí rẹ ó di sí gbogbo ìròyìn ohun tó ń lọ ní Naijiria àti káàkiri àgbáyé. Mọ̀ nípa wọn lórí ìkànnì Whatsapp rẹ

Bí ètò ìsìnkú Pope Francis yóò ṣe wáyé àti àwọn èèyàn tí yóò wà níbẹ̀
Eto isinku Pope Francis yoo waye ni Vatican ni owurọ ọjọ Abamẹta.

NiMET dá ìyanṣẹ́lódì dúró, fún ìjọba ní gbèdéke láti dáhùn àwọn ìbéèrè wọn
Iléeṣẹ́ ìròyìn The Punch sọ pé ààrẹ ẹgbẹ́ àwọn ètò ìrìnnà òfurufú, Uzor Oluchi fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé wọ́n ti so ìyanṣẹ́lódì náà rọ̀ ná fún ọ̀sẹ̀ méjì.

Alàgbà ni ọkọ mi ní ṣọ́ọ̀ṣì, wòólì ni mí fún ogún ọdún kí ń tó di Yeye Olokun - Omolara Fanimokun
Arabinrin Omolara ṣalaye ninu ifọrọwanilẹnuwo to ṣe pẹlu BBC Yoruba wi pe oun ṣe ẹsin musulumi ri, bakan naa loun tun lo ogun ọdun ni ṣọọṣi gẹgẹ bii wolii ijọ kan ki oun to wa gba ibi iṣẹ ti ori ran oun lọ eyi ti i ṣe bibọ okun.

Iléeṣẹ́ ológun bẹ̀rẹ̀ ìgbésẹ̀ ọ̀tun lóri ẹgbẹ́ agbébọn Mahmuda tó n ṣoro ní Kwara
O sọ eyi lasiko to n ba awọn Ologun sọrọ nigba to ṣe abẹwo si baraka Ologun to wa ni Sobi niluu Ilorin, to jẹ olu ilu ipinlẹ Kwara.

'A kàn ṣàdédé rí àwọn agbébọn tí wọ́n ṣíná ìbọn bolẹ̀, pa èèyàn mẹ́jọ, inú ìbẹ̀rù là ń gbé báyìí'
Ejire-Adeyemi sọ pé ni nǹkan bíi aago mẹ́sàn-án àbọ̀ alẹ́ ọjọ́ Ajé, ọjọ́ Kọkànlélógún, oṣù Kẹrin, ọdún 2025 láwọn agbébọn náà yawọ ibùdókọ̀ náà tí wọ́n sì ṣíná ìbọn bolẹ̀ sáwọn èèyàn tó ń gbafẹ́ ní ilé ìgbafẹ́ kan tó wà ní ẹ̀gbẹ́ ibùdókọ̀ náà.

Ẹ fura o! Èèyàn 135,000 ló ní HIV l'Eko nìkan - Wo bí o ṣe lè dáàbò bo ara rẹ
Ajọ NACA ni kaka ko san lara orilẹede Naijiria nipa aarun HIV, nise ni iye awọn to n ko aarun naa ni Naijiria n pọ sii.

Báwo ni àwọn ohun èèlò ìkunjú tí ò ń lò ṣe burú sí?
Báwo ni o ṣe máa ń fọ àwọn búrọ̀ṣì tí ò ń lò láti fi kun ojú? Ṣé o ti yá másíkárà ọ̀rẹ́ ẹ̀ rẹ rí tàbí lo ìtọ́tè wo níbi tí ó ti fẹ́ rà á? Èwo nínú àwọn ohun èèlò ìkunjú rẹ ni àwọn kòkòrò àìfojúrí wà nínú rẹ̀ jùlọ - ṣé másíkárà ni, tìròó, kàìnkàìn tàbí àwọn búrọ́ọ̀ṣì?

Ṣé lóòótọ́ ni pé ilé ejọ̀ ní kí wọ́n fi Simon Ekpa ránṣẹ́ sí Naijiria?
Saaju ni Ijọba apapọ kede pe adari ẹgbẹ IPOB to n ja fun ominira orilẹede Biafra, Simon Ekpa, atawọn mẹrindinlogun mii n ṣatilẹyin owo fawọn agbesunmọmi ni Naijiria.

Ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa ẹgbẹ́ agbébọn Mahmuda tó ń ṣoro nípìnlẹ̀ Kwara
Bẹẹ ba gbagbe,Ileeṣẹ ọlọpaa nipinlẹ Kwara ni awọn ti bẹrẹ iwadii lori awọn agbebọn to ṣe ìkọlu si ibudokọ kan ni Ilesha Baruba,

Báwo ni wọ́n ṣe ń yan Póòpù tuntun?
Ti asiko ba ti to lati yan Poopu tuntun ni wọn maa ke pe gbogbo awọn cardinal lati wa si Vatican, ni Rome.

Pásítọ̀ kó sí gbaga fún ṣíṣe aṣemáṣe pẹ̀lú ọmọdé tó jẹ́ àkàndá l'Ondo
Iléeṣẹ́ ààbò Amotekun ní àwọn ti bẹ̀rẹ̀ ìwádìí lórí ẹ̀sùn náà látàrí bí pásítọ̀ ọ̀hún ṣe jiyàn wí pé òun fún ọmọ náà lóyún.

Afurasí tó ń ṣagolo-ṣàgò gún ọmọ-ọmọ olórin Asiko, Comfort Omoge pa l'Ondo
''Lopopona Ayeka si Igbokoda ni ede-ai-yede ti bẹ silẹ laarin oloogbe OgoOluwa ati Mohammed to n ṣagolo.''

Èyí ni ìdí tí mo ṣe fi iṣẹ́ Fada sílẹ̀ nínú ìjọ Àgùda, tí mo sì di oníṣẹ̀ṣe
Ninu ifọrọwanilẹnuwo ti o ṣe pẹlu BBC Igbo, Obiagbaosogu sọ pe ki i ṣe nitori ki oun le lanfaani lati maa ba obinrin ni ibalopọ loun ṣe fi iṣẹ Fada silẹ gẹgẹ bi ọpọ eeyan ṣe ro.

Ọmọ Ghana mẹ́sàn án tí wọ́n fi iṣẹ́ tàn kúrò nílé, bá ara wọn nígbèkùn ní Mowe, nípìnlẹ̀ Ogun
Atẹjade ti So-Safe fi ṣọwọ si BBC, ṣalaye pe inu ile oniyara mẹta kan to wa lagbegbe Oke Sioni, ni Mowe ni wọn ti awọn ọmọ Ghana naa mọ.

Francis, ẹ̀ṣọ́ aláàbò nílé ijó tó di Póòpù tó mú àyípadà ńlá bá ìjọ Kátólíìkì
Oun ni Poopu akọkọ to wa lati ilẹ America tabi Hemisphere. Lati ọdun 741 ti Gregory III lati syria, ti ku, ẹnikẹni ti kii ṣe ọmọ ilẹ yuroopu ko jẹ Poopu.

Ṣe ó ṣeéṣe kí wọ́n yan Póòpù tuntun láti Africa?
Ni Afrika, ijọ ọhun pọ si ni ida 3.31% laarin ọdun 2022 si 2023, ti atẹjade lati Vatican si fi han pe pe 20% awọn ọmọ ijọ naa lo n gbe ni Afrika.

Kìnìún wọ ilé onílé, ó pa ọmọ ọdún mẹ́rìnlá
Àjọ tó ń rí sí ọ̀rọ̀ àwọn ẹranko aginjù ní Kenya, Kenya Wildlife Service, KWS sọ pé ní ilé ìgbé àwọn ọmọ náà, tí kò jìnà síbi igbó ọba tí kìnìún ọ̀hún wà, ló ti ṣe ìkọlù si.

Àwọn ajínigbé ṣọṣẹ́ ní Kwara, jí gbogbo èèrò inú ọkọ̀ gbé
Ọkan lara awọn olugbe ilu Obbo Aiyegunle to ba BBC News Yoruba sọrọ, Ọgbẹni Layọde salaye pe awọn ajinigbe naa ko awọn agbalagba to wa ninu ọkọ naa lọ amọ ti wọn fi awọn ọmọde silẹ.

HUMILITASCharleans' Contribution Worldwide

300

Charlean Doctors

250

Charlean Engineers

150

Charlean Lawyers

109

Charlean Professors

We always perform at our best when we work together

Our mission is to provide the means & technical know-how to accomplish the aforementioned with HUMILITAS - always