Iroyin sọ pe bi Fayemi ṣe ri Aarẹ nibi to jokoo si pẹlu awọn olori orilẹede mi-in, o sọ fun Peter Obi pe ko jẹ k'awọn lọọ fi ọla fun ẹni to tọ si, kawọn lọọ ki aarẹ Naijiria.
Perimenopause jẹ́ àsìkò tó máa ń wáyé ṣáájú kí obìnrin má tò rí nǹkan oṣù mọ́, nígbà tí àwọn ẹ̀yà ara obìnrin bá ń yípadà, táwọn ẹ̀yà ara tó wà fún ọmọ bíbí bá ń lọ sílẹ̀.
Adarí àjọ tó ń rí sí ìṣẹ̀lẹ̀ pàjáwìrì ní ìpínlẹ̀ Niger ìyẹn Niger State Emergency Management Agency, NSEMA, Abdullahi Baba-Arah ló kéde ìròyìn náà nínú àtẹ̀jáde kan tó fi léde Àìkú.
Ninu oṣu Kinni ọdun 2025 yii ni ajọ kan ti kii ṣe ti ijọba kede pe oun yoo san £20,000 fun ẹnikẹni to ba le ṣamọna bi ijọba yoo ṣe ri iya tabi awọn obi ọmọ naa.
Lásìkò tí wọn ń bá BBC Yorùbá sọ̀rọ̀, Bode Durojaye tíí ṣe Agbẹnusọ fún Aláàfin Oyo àti Nurudeen Akinade, Baálẹ̀ fún àwọn Mọ̀gàjí ilẹ̀ Ibadan sọ òkò ọ̀rọ̀ lu ara wọn pẹ̀lú ìtàn ńlá.
Kleinhaus ati ọpọ eeyan mi-in ti wọn jẹ alawọ funfun lati South Africa di ero ilẹ America, labẹ iṣakoso Aarẹ Donald Trump. Aarẹ sọ pe oun fẹẹ da aabo bo wọn kuro nibi iyasọtọ, idẹyẹsi ti wọn n koju, bo tilẹ jẹ pe South Africa ti sọ pe ko sohun to jọ bẹẹ lọdọ awọn.
Opesusi Oluwafemi, tíí ṣe bàbá Faith, ọmọbìnrin tó pa ara rẹ̀ torí máàkì kékeré tó gbà nínú èsì ìdánwò JAMB, bá BBC sọ̀rọ̀ nípa bí ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣe wáyé, irú èèyàn tí ọmọ rẹ̀ jẹ́ àti ipò ìbànújẹ́ tó ẹbí rẹ̀ wà.
Kọmisona feto ẹkọ ni ipinlẹ Kwara, Ọgbẹni Ọlọhungbẹbẹ Lawal, ṣalaye ninu atẹjade kan to fi sita pe ijọba ti awọn ile ẹkọ naa latari aawọ to bẹ silẹ laarin awọn akẹkọọ lati ile ẹkọ mejeeji.
Nínú fídíò kan tó gba orí ayélujára ni àwọn èèyàn kan ti ń bèèrè lọ́wọ́ afurasí náà tó pe ara rẹ̀ ní Pedro pé kí ló wá ṣe ní agbègbè náà tó sì ń fún wọn lésì pé òun fẹ́ jí ọmọ gbé ni.
Nínú fọ́nrán ohùn àti àwòrán kan tó gba orí ayélujára, ni gbajúmọ̀ òṣèré tíátà, Jumoke George pẹlu omije loju ṣalaye pe, ọdun kẹrin ree ti ọmọ rẹ obinrin ti di awati, to si tun da ọmọ meji silẹ fun oun lati maa tọju wọn.
Ero awọn eeyan tẹlẹ ni pe ologun Naijiria pẹlu ajọṣepọ awọn orilẹede alamuleti, ti ṣẹgun Boko Haram, ṣugbọn ni bayii, ikọlu naa n waye leralera lati nnkan bii ọdun mẹta sẹyin.
O le lọgọrun-un fidio bayii ti wọn lo imọ ẹrọ ti a mọ si AI ṣe, eyi to n ṣafihan Traoré bii akọni ọmọ ilẹ Afrika, ọpọ rẹ lo jẹ pe oun ti ko ri bẹẹ ni wọn n sọ. Ọpọlọpọ fidio bayii lo ti kun ori ayelujara kaakiri ẹkun Sahara ilẹ Africa lati ipari oṣu Kẹrin.
We have put an assorted mix of pics here for your enjoyment. We are always hungry for more - so if you have taken or have
access to some pics remotely related to our issue, please do not hesitate to send them to the web admin team