We Are The Charleans

International News - A Yoruba Perspective

From BBC


Wo iye ìgbà tí Portable ti kó sí wàhálà òfin
O ti tori awọn awuyewuye to n waye yii padanu awọn ode ere, ṣugbọn ariwo ko tori ẹ tan lẹyin ariwo.

Ajínigbé mẹ́rin pàdé ikú lọ́wọ́ ọlọ́pàá Ogun ní márosẹ̀ Eko sí Ibadan
CSP Omolola Odutola, Alukoro ọlọpaa Ogun to fi atẹjade iṣẹlẹ naa sita, ṣalaye pe yatọ si awọn to di oloogbe, awọn ajinigbe kan naa fara gba ọta ibọn, wọn si gbe ọta ibọn sa lọ.

Nítorí ọjọ́ iwájú Naijiria la ṣe pa Ọgagun Vatsa, ọ̀rẹ́ mi ìgbà èwe-IBB
Ẹsun naa ni IBB sọ pe o foju han kedere pe Vatsa lọwọ nibẹ, ati pe oun gan-an lo sanwo fun awọn ṣọja yooku lati wa ọna ti wọn yoo fi ditẹ gba ijọba mọ oun lọwọ.

Hamas tú méjì nínú mẹ́fà ọmọ Ísírẹ́lì tó wà ní àhámọ́ sílẹ̀ lónìí
Iroyin to tẹ wa lọwọ ni awọn mọlẹbi awọn eeyan naa ti wọn gbe ọkan soke ti wọn si n reti lati tẹwọgba awọn eeyan wọn.

A máa lo ọ̀nà míràn láti gba ìdájọ́ b'íjọba bá já wa kulẹ̀- Bàbá Yetunde tí wọ́n bá òkú rẹ̀ nílé ààfáà n'Ilorin
Baba Hafsat ni oun mọ pe ilu yii le ti oun ko si fẹ sọ ohun ti mọlẹbi n gbero ṣugbọn oun fẹ ki ileeṣẹ ọlọpaa ri pe wọn fun awọn ni idajọ ododo.

"Ọlọ́pàá ti ilẹ̀kùn ọọ́físì àjọ elétò ìdìbò Osun, fi ṣìkùn òfin mú òṣìṣẹ́ rẹ̀"
Bẹẹ ba gbagbe, ana ni Gomina Ademola Adeleke kede pe mimi kan o mi wiwaye eto idibo ijọba ibilẹ naa nipinlẹ Osun lonii.

Wọ̀nyí làwọn ohun tó sọ ''June 12'' di mánigbàgbé ní Nàìjíríà títí di òní
Tolori-tẹlẹmu lo dibo naa fun MKO Abiola lai ruju, gbogbo awọn ayẹbowo lo si fidi ẹ mulẹ pe Abiola lo jawe olubori.

Mìmì kan kò lè mi ètò ìdìbò ìjọba ìbílẹ̀ Osun tí yóò wáyé lọ́la - Adeleke
Gomina sọ eyi lasiko to n gba alejo ajọ to n ṣamojuto eto idibo ni ọfiisi rẹ lowurọ ọjọ Eti, ọjọ kọkanlelogun oṣu keji ọdun 2025.

Ìwádìí BBC tú àṣírí bí iléeṣẹ́ apòògùn India kan ṣe ń kó òògùn olóró Opioid wọ Nàìjíríà, Ghana àti Ivory Coast
Ko si orilẹede ti wọn ti faye gba tita oogun yii fun araalu, koda, o maa n ṣokunfa ki eeyan ma lee mi daadaa ati giri.

Àìsàn òtútù igbáàyà ló mú Pope Francis nínú ẹ̀dọ̀fóró méjèèjì
Pẹlu gbogbo eyi, Vatican ni Pope si wa ni erogba gida, to si n lo gbogbo asiko rẹ lojumọ lati ka iwe, sinmi ati gbigba adura.

Àlàyé ohun tójú Portable rí fún wákátí mẹ́rin kó tó rí béèlì gbà, àti ẹni tó ṣe onídúró fún un rèé
Bi gbogbo eto beeli naa ṣe pari ni nnkan bi agogo mẹrin kọja iṣẹju mejidinlọgbọn, ni wọn mu Portable jade sita kootu, to si lọ dupẹ lọwọ adajọ to buwọ lu iwe beeli naa fun un.

Ẹja gbé arákùnrin kan mì, ló bá tún pọ̀ ọ́ sílẹ̀
Leti okun Chilean Patagonia ni oun ati baba rẹ lọ nigba ti iṣẹlẹ naa ṣẹ.

Primeboy ń béèrè N50m lọ́wọ́ ìyá Mohbad, ó ní ó ba òun lórúkọ jẹ́
Loju opo Instagram rẹ, Prime Boy tun kede l’Ọjọruu, ọjọ kọkandinlogun oṣu Keji ọdun 2025 yii, pe oun n wọ Iya Mohbad lọ sile ẹjọ

Ṣáká lara mi dá, mi ò lárùn ọpọlọ o - Portbale sọ̀rọ̀ níwájú adájọ́
Ọjọru to kọja ni Portable jọwọ ara rẹ fun ọlọpaa nipinlẹ Eko, ko to di pe wọn fa a le awọn ọlọpaa ipinlẹ Ogun lọwọ.

Nítorí ọjọ́ iwájú Naijiria la ṣe pa Ọgagun Vatsa, ọ̀rẹ́ mi ìgbà èwe-IBB
Ẹsun naa ni IBB sọ pe o foju han kedere pe Vatsa lọwọ nibẹ, ati pe oun gan-an lo sanwo fun awọn ṣọja yooku lati wa ọna ti wọn yoo fi ditẹ gba ijọba mọ oun lọwọ.

Ọlọ́pàá kú sẹ́nu iṣẹ́, òkú rẹ̀ di ariwó láàrín mọ̀lẹ́bí àti iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ní ìpínlẹ̀ Ondo
Ọjọ keji ọdun keresi ni oloogbe naa kuro nile, amọ oku rẹ ni wọn gbe wale lẹyin ọyọ diẹ.

Wo bí iléeṣẹ́ ìròyìn RT tí Russia ń ṣàtìlẹyìn fún ṣe ń ṣe ìdánilẹ́kọ̀ọ́ fáwọn akọ̀ròyìn ilẹ̀ Afirika
Ileeṣẹ iroyin RT ti wọn le kuro ni Yuroopu ati Amẹrika, ti wọn si kede ijiya to tọ fun wọn lori ẹsun pe wọn n gbe iroyin ofege ko bikita rara nipa sisọ oniruuru iroyin ofege fawọn to wa nibi idanilẹkọọ naa.

Èyí lohun tí a mọ̀ nípa Tọkọ-taya tó pa ara wọn l'Ekiti àti ìdí abájọ
Iroyin sọ pe awọn tọkọ-tiyawo naa pa ara wọn ni.

Mi ò kú o, mi ò sí rí ẹ̀wọ̀n he rárá – Gbajúmọ̀ òṣèrè, Dele Odule figbeta lórí àwọn tó ń gbé ìròyìn ikú rẹ̀ kiri
Dele Odule lo sọrọ naa ninu fidio kan to di lede loju Instagram rẹ, nibi to ti bu ẹnu atẹ lu awọn kọlọrọsi to n gbe iroyin aburu kiri nipa oun.

Oriyomi Hamzat kọ́ ilé tuntun fún gbajúmọ̀ òṣèré, Iya Niwe n'Ibadan, ló bá bú sẹ́kún
Nínú fídíò náà, Iya Niwe tó ń wa ẹkún mu ní òun kò mọ ẹni tí yóò bá òun dúpẹ́ fún oore ńlá tí Oriyomi Hamzat ṣe fún òun.

Ẹ gbọ́dọ̀ kéde ohun ìní yín títí ìparí oṣù Kẹ́ta tàbí kí ẹ jìyà, Ààrẹ Mahama sáwọn tó yàn sípò
Aarẹ John Mahama orilẹede Ghana sọrọ yii lẹyin to fi iwe to fi kede ohun ini rẹ ṣọwọ si ayẹwe owo wo agba orilẹede naa lọjọ kejidinlogun oṣu Keji yii.

Ẹ má wò mí níran, ìfúnpá mi ti wọ 157, nǹkan ti yí wọ́ fún mi – Òṣèré Tíátà Hamima Abubakar pariwo síta
Halima ni o ti le ni ọdun mẹfa ti oun ti kopa ninu sinima gbẹyin.

Àbọ̀ ìpàdé láàrin Amẹrika àti Russia lórí ọ̀nà láti dá ogun pẹ̀lú Ukraine dúró rèé
Ṣaaju ni Russia ati Amẹrika ti buwọlu adehun lati jiroro lori dida ogun naa duro.

Gbogbo èrò inú bàlúù tó já, dojúdé l'Ámẹ́ríkà ló móríbọ́
Àwọn aláṣẹ sọ pé èèyàn mejìdínlógún ló farapa nínú ìjàmbá ọ̀hún, tó fi mọ́ ọmọdé àtàwọn àgbàlagbà méjì tí ìfarapa wọn lágbára gidi.

Ṣé lóòtọ́ ní amòfin àgbà Nàìjíríà ti pàṣẹ káwọn agbófinró dẹ́kun fífojú àwọn afurasí ọ̀daràn hàn?
Nigba ti awọn akọroyin kan si awọn ọga ọlọpaa lori ọrọ naa, wọn ni ọrọ ọhun ti to awọn leti.

Ilé ẹjọ́ Kòtẹ́milọ́rùn gbé ìdájọ́ kalẹ̀ lórí ìyànsípò Ọba Ghandi Olaoye gẹ́gẹ́ bíi Soun Ogbomoso
Igbimọ onidajọ ẹlẹni mẹta ti Ile ẹjọ kotẹmilọrun niluu Ibadan ti Adajọ Yargata Nimpar dari wọn yi idajọ ile ẹjọ giga danu, eyi to fagile Ọba Olaoye gẹgẹ bii Soun ilu Ogbomoso.

Ẹ jìnà sáwọn ìjọba ìbílẹ̀ gbogbo l'Osun o, Adeleke ké sáráàlú lẹ́yìn tí èèyàn mẹ́fà kú níbi wàhálà káńsù
Ìdarí Adeleke yìí ló ń wáyé lẹ́yìn tí wáhálà bẹ́ sílẹ̀ ní ìpínlẹ̀ náà lọ́jọ́ Ajé nígbà táwọn alága ìjọba ìbílẹ̀ tí ilé ẹjọ́ dá láre ní ọ̀sẹ̀ tó kọjá gbìyànjú láti gba ipò wọn padà.

Ṣíṣe irun 'dreadlock', gbígbé ṣòkòtò sí bẹ̀bẹ̀rẹ́ ìdí, lílo ìlẹ̀kẹ̀ ìdí àtàwọn ìmúra míràn tí ìjọba ìbílẹ̀ Owo sọ̀ di èèwọ̀ nínú òfin tuntun tó jáde
Alaga kansu ti wọn ṣẹṣẹ dibo yan ni ijọba ibilẹ naa, Alagba Tope Omolayo, lo fi awọn ofin ọhun sita ninu atẹjade kan, eyii to tẹ akọroyin BBC Yoruba lọwọ.

Wo ibi tí ìgbẹ́jọ́ ẹ̀sùn ìbanilórúkọjẹ́ tí Falana pe VDM dé dúró
Adajọ Matthias Dawodu sun igbẹjọ ọhun siwaju lẹyin to gba lẹta lati ọwọ agbẹjọro VDM, Deji Adeyanju.

Kí ni àdínkù ìdá mẹ́wàá tí NBS kéde pé ó bá ọ̀wọ́ngógó túmọ̀ sí?
Àtẹ̀jáde ti NBS fi sójú òpó wọn lórí ìkànnì ayélujára X lọ́jọ́ Ìṣẹ́gun, ọjọ́ Kejìdínlógún, oṣù Kejì, ọdún 2025 ní àdínkù ìdá mẹ́wàá (10.32%) ló bá ọ̀wọ́ngógó nínú oṣù Kìíní ọdún 2025.

Èèyàn mẹ́fà ló kú lásìkò wàhálà tó wáyé láwọn ìjọba ìbílẹ̀ l'Osun lọ́jọ́ Ajé – Ọlọ́pàá
Ninu atẹjade kan lọjọ Iṣẹgun, alukoro ileeṣẹ ọhun, Yemisi Opalola ba awọn to padanu ẹmi wọn atawọn ti dukia wọn ba iṣẹlẹ ọhun lọ kẹdun.

Ààfáà Abdurahman, afurasí tí wọ́n bá òkú Yetunde nílé rẹ̀ n'Ilorin fojú balé ẹjọ́, dèrò ẹ̀wọ̀n
Adajọ S.B. Muhammed sọ pe ọjọ kẹfa oṣu kẹta ọdun yii ni igbẹjọ yio bẹrẹ ni pẹrẹu, to si pasẹ pe ki wọn ko awọn afunrasi naa si ahamọ ọgba ẹwọn Okekura ni ilu Ilọrin.

''Alárùn ọpọlọ ni mí kódà Aro ni mo ti ń gba ìtọ́jú,'' Portable sọ̀rọ̀ lẹ́yìn tí ọlọ́pàá kéde pé àwọn ń wá a
Portable ni ki wọn fi oun silẹ tori alarun ọpọlọ loun, atipe ọmọ ijọba loun jẹ gẹgẹ bii alarun ọpọlọ.

Oriyọmi Hamzat àti Naomi Ṣilẹkunọla fara hàn níléẹjọ́ lonii, bí ìgbẹ́jọ́ náà ṣe lọ rèé...
Ile ẹjọ Majistreeti to n bẹ ni agbegbe Iyaganku niluu Ibadan lo kọkọ pasẹ wi pe ki wọn sọ awọn afurasi naa si atimọlẹ ko to di pe ọrọ naa de ile ẹjọ giga ipinlẹ Ọyọ nibi ti wọn ti gba beeli wọn ni ibẹrẹ ọdun yii.

Ọmọ ẹgbẹ́ PDP méjì kú, alága APC kan dèrò ọ̀run níbi aáwọ̀ tó bẹ́ sílẹ̀ l'Osun lórí ọ̀rọ̀ ìjọba ìbílẹ̀
Laarọ ọjọ Aje lawọn alaga ijọba Ibilẹ APC ti ile ẹjọ kotẹmilọrun da lare gba awọn ofiisi awọn ìjọba ibilẹ lọ eyi to mu kawọn ọmọ ẹgbẹ PDP tako wọn ti aawọ si bẹ silẹ kaakiri ipinlẹ Osun.

Ìdí tí àjọ DSS fi ya wọ ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin Eko lọ́jọ́ Ajé
Lẹyin o rẹyin, awọn aṣofin ati olori ile pada jokoo, nibi ijokoo naa si ni wọn ti kede wi pe gbọin gbọin lawọn wa lẹyin Meranda.

Wọ́n yìnbọn pa Ìmáàmù àkọ́kọ́ tó fojú hàn bíi olólùfẹ́ akọ-sákọ lágbàáyé
Laarọ ọjọ Abamẹta ọjọ kẹẹdogun oṣu Keji ni wọn pa Hendricks lẹyin tawọn eeyan kan da ọkọ ti o n rinrin ajo ninu rẹ lọna lẹgbẹ ilu Gqeberha lorilẹede South Africa.

Kóòtù yọ̀ǹda ọkùnrin tó fi ìbálòpọ̀ pa ìyàwó rẹ̀, ariwo ta
Lọjọ Aje to kọja yii ni Adajọ Narendra Kumar Vyas, ti ile ẹjọ giga to wa ni Aarin-Gbungbun India, ni Chhattisgarh, yi idajọ 2019 pada, to si ni ki ọkọ iyawo naa maa lọ sile rẹ layọ ati alaafia.

Àwọn ọ̀dọ́ jó àgọ́ ọlọ́pàá lẹ́yìn tí wọ́n fẹ̀sùn kàn pé wọ́n pa èèyàn kan sí àgọ́ wọn
Gẹ́gẹ́ bí ìròyìn tó tẹ̀ wá lọ́wọ́, wàhálà bẹ́ sílẹ̀ ní ìlú náà lẹ́yìn táwọn igun ọ̀dọ́ méjì kan fìjà pẹ́ẹ́ta ní àyájọ́ olólùfẹ́ tó wáyé lọ́jọ́ Ẹtì.

Àìsàn sémìí-sémìí, Asthma ló pa Yetunde, mo kan gé e wẹ́lẹ̀wẹ̀lẹ nítorí ẹ̀rù tó bà mí ni – Ààfáà Mohammed Bello
Awọn mọlẹbi oloogbe naa n sọrọ, wọn ni irọ pọnbele ni afurasi naa n pa nitori ọmọ awọn ko ni arun semi-semi ṣaaju iṣẹlẹ naa.





We always perform at our best when we work together

Our mission is to provide the means & technical know-how to accomplish the aforementioned with HUMILITAS - always



This Section Can Accommodate Your Adverts





Charleans In Celebration Mode

We have put an assorted mix of pics here for your enjoyment. We are always hungry for more - so if you have taken or have access to some pics remotely related to our issue, please do not hesitate to send them to the web admin team

SCOBA PARTNERS

corporates and enterprise businesses we have the pleasure to connect with.